Enimere Àkànbí
Ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Shooting Stars Sports Club, 3SC ilẹ̀ Ìbàdàn bá ìjákulẹ̀ pàdé nínú ìfigagbága tí wọ́n fi ṣíde sáà 2025/2026 líìgì oríléèdè Nàìjíríà, NPFL.
Ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Bayelsa United, ló wá kan 3SC lábùkù lójú àwọn olólùfẹ́, alátìlẹyìn àti alákóso wọn pẹ̀lú àmì ayò kan sí òfo, ní pápá ìṣerédárayá Lékan Sàlámì, ní ìlú Ìbàdàn.
Ìfigagbága náà ló jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí Nurudeen Awẹ́roro, yóó má a tukọ̀ 3SC, nínú líìgì oríléèdè Nàìjíríà, láti ìgbà tí ó ti tẹ́wọ́ gba iṣẹ́ náà, lábẹ́ ìṣàkóso Ọnọrábù Táíwò Lékan-Sàlámì.
Àwọn ojú tuntun tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ darapọ̀ mọ́ 3SC ni ó pọ̀jù nínú àwọn agbábọ́ọ̀lù tí akọ́nimọ̀ọ́gbá, Awẹ́roro, tó tukọ̀ Ìkòròdú City ní sáà tó kọjá, kó sí orí i pápá, kojú u Bayelsa United.
Bí ìfigagbága ọ̀hún ṣe wọ ọgbọ̀n ìṣẹ́jú ni Lawal Kẹ́hìndé, mi àwọ̀n fún ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Bayelsa United, tí Ṣútìn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣe máa ń pèé, kò sì leè ta pútú.
Ní báyìí, Ọgbọ̀njọ́ oṣù yìí, ni 3SC yóó rìnrìn àjò lọ sí ìpínlẹ̀ Edo, láti kọjú Bendel Insurance tí òhun náà pàdánù sí ọwọ́ ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù El-Kanemi Warriors, nígbà tí Bayelsa United, yóò gba Barau tó ta ọ̀mì pẹ̀lú u Enyimba, lálejò ní Ọjọ́kọkànlélọ́gbọ̀n.
3SC Sá Kíjokíjo Nílùú Ìbàdàn Níwájú Bayelsa United, Tó Wá Fogun Jà Wọ́n Ní Ìfigagbága Àkọ́kọ́ NPFL
3SC Sá Kíjokíjo Nílùú Ìbàdàn Níwájú Bayelsa United, Tó Wá Fogun Jà Wọ́n Nínú Ìfigagbága Àkọ́kọ́ NPFL











Leave a Reply